Yakubu Adesokan ṣe oríire

Ìwúrí àti àyọ̀ nlá ni fún gbogbo ọmọ Yorùbá àti gbogbo Nàìjíríà lápapọ̀ lónìí! Ọmọ ìyá wa Yakubu Adesokan ló mà fúnwa láyọ̀ o. Adesokan jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn eléré ìdárayá wa tí Nàìjíríà rán lọ́ ibi ìdíje Paralymics tó nlọ lọ́wọ́ lọ́wọ́ báyìí ní ìlú London. Arọ ni alákùnrin yìí jẹ́, iye ọjọ́ orí i rẹ̀ sì nṣe mẹ́tàlélọ́gbọ̀n. Ẹré tirẹ̀ jẹ́ ìdíje ìgbẹ́rùwíwo sókè.

Lásán kọ́ ni pé alákùnrin yìí gbé ipò kíní, ìyẹn ni pé ó gba wúrà, ìwọ̀n ẹrù tó rí gbé sókè, kò tíì sí ẹni ẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ kankan tó gbé ìwọ̀n wíwo báyìí rí! Ìyẹn ni pé láti ìgbà tí ìdíje yìí ti bẹ̀rẹ̀, Yakubu ni ipò kíní pátápátá. Àb'ẹ́ẹ̀ rí nkan?

Ọjọ́ ìkíní rèé o, a ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀. 'Ó tún kù!' ni ìbọn nró!

Comments

Popular posts from this blog

Kíni ìtumọ̀ "SIM Card" l’édè Yorùbá?

Etí òkun ìgbafẹ́

Mojúbà o!